Home Uncategorized Emefiele kan ìjàngbọ̀n! – The Nation Newspaper

Emefiele kan ìjàngbọ̀n! – The Nation Newspaper

by admin

Ilé-ẹjọ́ ní kò le lọọ gbàtọ́jú lókè-òkun

By Kayọde Ọmọtọṣọ

Lanaa, ọjọ Iṣẹgun, Tusidee, ni ile-ẹjọ giga ijọba apapọ to wa niluu Mataima, Abuja, ni gomina ileefowopamọ agba ilẹ wa tẹlẹ, Godwin Emefiele, ko lẹtọọ lati lọọ gbatọju loke-okun. Adajọ Hamza Muazu, ni pe Emefield ko ko awọn ẹri to to silẹ lati fihan pe ewu wa fun un ti ko ba rinrinajo lọ soke-okun fun itọju ara rẹ.

Adajọ ni pe loootọ, Emefiele ni pe awọn dokita oun ranṣẹ pe oun fun itọju ṣugbọn ko fi iwe ti wọn fi ranṣẹ pe e ṣọwọ sile-ẹjọ gẹgẹ bi ẹri. Adajọ Muazu ni gomina tẹlẹ nileefowopamọ agba ilẹ wa yii ko fi ẹri kalẹ pe ko si ileewosan kankan lorileede Naijiria to le ṣetọju aisan to n ṣe e. Adajọ ni “ile-ẹjọ ọtọọtọ mẹta ni olujẹjọ ti n jẹjọ lọwọ lori ẹsun iwa ọdaran, idi niyẹn to fi yẹ ki ile-ẹjọ mọ idi to fi fẹẹ lọọ gbatọju ni pato, eyi ti ko fihan ile-ẹjọ titi di asiko yii. Nitori idi eyi, ẹbẹ olujẹjọ ko nitumọ rara, a si fagile e.”

You may also like

Leave a Comment

Welcome to DopeReporters, the leading resource for accurate, timely, and influential news. Covering important events in Nigeria and around the world is part of our mission to create stories that have an impact. Giving you a comprehensive perspective on politics, sports, entertainment, current events, and more is our goal. 

Edtior's Picks

Latest Articles

©2022 DopeReporters. All Right Reserved. Designed and Developed by multiplatforms